Àwọn Òǹkọ̀wé Yorùbá

Kọ́lá Akínlàdé

Ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹfà, ọdún 1924 ni wọ́n bí Kọ́lá Akínlàdé ní ìlú Ayétòrò ní ìpínlẹ̀ Ògùn. Orúkọ àwọn òbí rẹ̀ ni Michael Akínlàdé àti Elizabeth Akínlàdé. Iṣẹ́ àgbẹ̀ ni iṣẹ́ tí Michael Akínládé ń ṣe. Láàrín 1933 sí 1938, Kọ́lá Akínlàdé lọ sí Ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ St. Paul, Ayétòrò.
Ó ṣiṣẹ́ oko láti ọdún 1939 sí 1945 nítorí kò rí owó láti tẹ̀ síwájú nídìí ẹ̀kọ́. Nígbà tó ó di ọdún 1945, ó pa iṣẹ́ oko tì láti lọ di akọlẹ́tà fún gbogbogbòo. Nígbà tí ó dé ìlú Ìlaròó, iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí akọlẹ́tà fún gbogbogbòo sọ ọ́ di ẹni tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́pàá, àwọn ọ̀daràn, àwọn afunrasí, àwọn agbẹjọ́rò, àti ilé-ẹ̀jọ́. Bákan náà, ó dá ilé-iṣẹ́ atẹ̀wétà sílẹ̀.

Joseph Fọlọ́runsọ́ Ọdúnjọ

A bí J.F. Ọdúnjọ ní ọdún 1904 ní ìlú Abẹ́òkúta. Ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ St. Augustine, Ìtésí, Abẹ́ọ̀kúta ni ó bẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ọdún 1914. Ó lọ kọ́ iṣẹ́ olùkọ́ni ní Catholic Teachers Training College, Ibadan ní ọdún 1920. Lẹ́yìn tí ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyé ní ọdún 1924, ó di ọ̀gá ilé-ìwé ní St. Augustine títí di ọdún 1939. Nígbà tí ó kúrò níbẹ̀, ó lọ di ọ̀gá ilé-ìwé ilé-ìwé St. Paul ní Ebute-Metta láti ọdún 1940 sí 1946. Láàárín ọdún 1948 sí 1952, ó ṣe iṣẹ́ káàkiri àwọn ilé-ìwé ní agbègbè Èkó àti Abẹ́òkúta.

Ọládẹ̀jọ Samuel Òkédìjí

Ìdílé Àpáàrà ní ìlú Ọ̀yọ́ ni wọ́n ti bí Ọládẹ̀jọ́ Òkédìjí ní ọdún 1929. Ọdún 1935 ni Òkédìjí bẹ̀rẹ̀ ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Methodist. Ilé-ìwé St. Andrew’s College Demonstration ni ó ti parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ọdún 1943. Òkédìjí ṣe iṣẹ́ olùkọ́ ní ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Fìdítì ní 1944 kí ó tó tẹ̀ síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀. Ó lọ kọ́ iṣẹ́ olùkọ́ni ní Wesley College ní Ìbàdàn. Ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ọdún 1948 pẹ̀lú ìwé ẹ̀rí Grade II.

Solomon Adébóyè Babalọlá

Wọ́n bí Adébóyè Babalọlá ní ìlú Ìpétumodù ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kéjìlá ọdún 1929. Ó kàwé gboyè ní ilé-ìwé Acimota College ní Ghana ní ọdún 1946. Lẹ́yìn tí ó gboyè àkọ́kọ́, ó ṣe iṣẹ́ olúkọni ní Ilé-ìwé Igbobi. Ní ọdún 1948 ó gba owó ìránwọ́ kejí láti ka ìwé ní ilé-ìwé Queen’s College, Cambridge, ó sì gba oyè rẹ̀ ní ọdún 1952. Nígbà tí ó gba oyè rẹ̀ ní Queen’s College, ó padà sí ìdí iṣẹ́ olúkọni ní Ilé-ìwé Igbobi. University of London ni ó ti gba oyè ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ (Ph.D.).

Àrínpé Gbékẹolú Adéjùmọ̀

Ọjọ́ kẹrin, oṣù kẹ́ta ọdún 1964 ní ìlú Módákẹ́kẹ́. Ó lọ sí ilé-ìwé Obafemi Awolowo University ní ọdun 1981 sí 1995 ó sì gba àwọn oyè imọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú èdè àti lítírésọ̀ Yorùbá. Láàárín ọdún 1988 sí 2003, ó ṣe iṣẹ́ olùkọ́ni ní University Adó-Èkìtì. Ọdún 2003 ni ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ olùkọ́ni ní University of Ibadan. Ó ti ìdí iṣẹ́ yìí di Ọ̀jọ̀gbọ́n nínú àwọn èdè àti lítírésọ̀ Yorùbá.

Scroll to Top